Jump to content

Joel Olaniyi Oyatoye

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Joel Olaniyi Ọyátóyè)

Ọmọ Ọba Joel Ọláníyì Ọyátóyè tí gbogbo ènìyàn mọ̀ sí Bàbá Àṣà, jẹ́ ọmọ bíbí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti Kánádà, ó jẹ́ akọ ewì, olùgbóhùnsafẹ́fẹ́, oníṣẹ́ ara-ẹni, ajíyìnrere, olùpolongo àti olùgbélárúgẹ àṣà àti ìṣe Yorùbá. [1]

Ibẹ̀rẹ̀ ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Ọláníyì ní Ìpínlẹ̀ Kwara ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ni 27 January, 1984 níbi tí ó ti lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ àti girama ṣáájú kí ó tó lọ sí orílẹ̀-èdè Canada láti lọ tẹ̀ siwájú nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀.

Ọyátóyè tí ó jẹ́ ọmọọba nífẹ́ sí gbígbé àṣà Yorùbá lárugẹ jákè-jádò agbáyé, pàá pàá jùlọ bí ó ṣe ma ń wọ aṣọ ìbílẹ̀ tí ó sì ń lo gbogbo ohun èlò ìbílẹ̀ Yorùbá láti fi pàtàkì àṣà Yorùbá hàn fáyé rí. Ọyátóyè jẹtọ́ àṣà òun ìgbéga Yorùbá láti kékeré láti ara bàbá rẹ̀ Olóyè Titus Ọyátóyè Títíloyè tí ó ti dolóògbé. Iya re Cicilia Oyatoye

Iṣẹ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ọyátóyè ṣàkíyèsí wípé iná àṣà àti ìṣe Yorùbá ti ń jó àjórẹ̀yìn, èyí kò sì bójúmu, àìbìkítà sí ìgbéga àṣà òun ìṣe Yorùbá lè ṣakóbá fún láti ròkun ìgbagbé. Èyí ni ó múmú láyà rẹ̀ tí ó fi ń gbé àdá Yorùbá lárugẹ. [2] Ifẹ́ rẹ̀ sí èdè Yorùbá ni ó mu kọ́ṣẹ́ nípa ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ láti lè ma polongo ohun ina àjogúnbá Yorùbá lórí afẹ́fẹ́. Ó ti ṣe àwọn ìṣeẹ́ àkànṣe nípa èdè, àṣà Yorùbá gẹ́gẹ́ olùgbóhùnsafẹ́fẹ́ pàá pàá jùlọ lórí àwọn ilé-iṣẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ bíi: Paramount FM tí ó wà ní ìlú Abẹ́òkúta, Radio Lagos tí ó wà ní ìlú Ìkẹjà, Choice FM . Ó gbajúmọ̀ fún [[ewì][ kíké, Rárá sísun, ìjálá, ẹkún ìyàwó sísun àti oríkì kíké.[3] Láti lè mú èrò àti àlá rẹ̀ ṣẹ, ó gbéra lọ sí orílẹ̀-èdè Canada láti lọ kẹ́kọ̀ọ́ tí ó sì ń ṣiṣẹ́ mọ. Ó lọ ilé ẹ̀kọ́ Red River College, àti Academic College tí àwọn méjèjì wà ní agbègbè Winnipeg ní ìlú Canada, O ko eko nipa Eto isiwa (Immigration Consultant) ni Ashton College British Columbia Canada. Ó ti ṣisẹ́ pẹ̀lú ilé-iṣẹ́ ààbò Impact Security láàrín ọdún 2013 sí 2015, bákan náà ni ó ti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú St Amant láàrín ọdún 2013 sí 2020 ní orílẹ̀-èdè Canada. Lati 2020 o ti n sise Ara re. O je Aare ati Oludasile Egbe ti a n pe ni Asa Day Worldwide Inc. Canada, ti n se igbe laruge Asa Yoruba kakiri agbaye, Oun si tun ni Oludasile ati alamojuto Asa Day Museum ni Canada.

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Daniels, Ajiri (2021-12-26). "Olaniyi Oyatoye: Young Yoruba art, culture enthusiast". The Sun Nigeria. Retrieved 2023-07-25. 
  2. "‘Why I am celebrating Yoruba culture in Canada’". Tribune Online. 2019-08-08. Retrieved 2023-07-25. 
  3. "Olaniyi Oyatoye: How I Ply my Cultural Promotion Trade". THISDAYLIVE. 2021-09-03. Retrieved 2023-07-25.